Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 25:5-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Dáfídì sì rán ọmọkùnrin mẹwàá, Dáfídì sì sọ fún àwọn ọ̀dọ́kùnrin náà pé, “Ẹ gòkè lọ sí Kámẹ́lì, kí ẹ sì tọ Nábálì lọ, kí ẹ sì kí i ni orúkọ mi.

6. Báyìí ni ẹ ó sì wí fún ẹni tí ó wà ni ìrora pé, ‘Àlàáfíà fún ọ! Àlàáfíà fún ohun gbogbo tí ìwọ ní!

7. “ ‘Ǹjẹ́ mo gbọ́ pé, àwọn olùrẹ̀run ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ Wò ó, àwọn olùsọ́ àgùntàn rẹ ti wà lọ́dọ̀ wa àwa kò sì pà wọ́n lára, wọn kò sì sọ ohunkóhun nù ní gbogbo ọjọ́ tí wọ́n wà ní Kámẹ́lì.

8. Bi àwọn ọmọkùnrin rẹ léèrè, wọn ó sì sọ fún ọ. Nítorí náà, jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí rí ojú rere lọ́dọ̀ rẹ; nítorí pé àwa sá wá ní ọjọ́ àṣè: èmi bẹ̀ ọ́ ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà, fi fún àwọn ìránṣe rẹ, àti fún Dáfídì ọmọ rẹ.’ ”

9. Àwọn ọmọkùnrin Dáfídì sì lọ, wọ́n sì sọ fún Nábálì gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní orúkọ Dáfídì, wọ́n sì sinmi.

10. Nábálì sì dá àwọn ìránṣẹ Dáfídì lóhùn pé, “Ta ni ń jẹ́ Dáfídì? Tàbí ta ni sì ń jẹ́ ọmọ Jésè? Ọ̀pọ̀lọpọ̀ iránṣe ni ń bẹ ni isinsinyìí tí wọn sá olúkúlùkù kúrò lọ́dọ̀ olúwa rẹ̀.

11. Ǹjẹ́ ki èmi o mú òunjẹ́ mi, àti omi mi, àti ẹran mi ti mo pá fún àwọn olùrẹ́run mi, ki èmi si fi fún àwọn ọkùnrin ti èmi kò mọ̀ ibi wọ́n ti wá?”

12. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin Dáfídì sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n, wọ́n sì pada, wọ́n sì wá, wọn si rò fún un gẹ́gẹ́ bi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.

13. Dáfídì sí wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Kí olúkúlùkù yín ó di idá rẹ́ mọ́ idi,” Olúkúlùkù ọkùnrin sì di idà tirẹ́ rẹ́ mọ̀ ìdí; àti Dáfídì pẹ̀lú sì di idà tirẹ̀; ìwọ̀n irinwó ọmọkùnrin si gòkè tọ Dáfídì lẹ́yin; igba si jókòó nibi ẹrù.

14. Ọkan nínú àwọn ọmọkùnrin Nabali si wí fún Ábígáílì aya rẹ̀ pé, “Wo o, Dáfídì rán oníṣẹ́ láti ihà wá láti ki olúwa wa; ó sì kanra mọ́ wọn.

15. Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà ṣe oore fún wa gidigidi, wọn kò ṣe wá ní ibi kan, ohunkóhun kò nù ni ọwọ́ wa ni gbogbo ọjọ́ ti àwa bá wọn rìn nígbà ti àwa ń bẹ lóko.

16. Odi ni wọ́n sáà jásí fún wa lọ́sànán, àti lóru, ni gbogbo ọjọ́ ti a fi bá wọn gbé, tí a n bojútó àwọn àgùntàn.

17. Ǹjẹ́, rò ó wò, kí ìwọ sì mọ èyí ti ìwọ yóò ṣe; nítorí pé a ti gbèrò ibi sí olúwa wa, àti sí gbogbo ilé rẹ̀; òun sì jásí ọmọ Bélíálì tí a kò le sọ̀rọ̀ fún.”

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 25