Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 25:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Sámúẹ́lì sì kú; gbogbo ènìyàn Ísírẹ́lì sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì sunkún rẹ̀ wọ́n sì sin ín nínú ilé rẹ̀ ní Rama.Dáfídì sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ijù Páránì.

2. Ọkùnrin kan sì ń bẹ ní Máónì, ẹni tí iṣẹ́ rẹ̀ ń bẹ ní Kámẹ́lì; ọkùnrin náà sì ní ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ní ẹgbẹ̀ẹ́dógún àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún ewúrẹ́: ó sì ń rẹ irun àgùntàn rẹ̀ ní Kámẹ́lì.

3. Orúkọ ọkùnrin náà sì ń jẹ́ Nábálì, orúkọ aya rẹ̀ ń jẹ́ Ábígáílì; òun sì jẹ́ olóye obìnrin, àti arẹwà ènìyàn; ṣùgbọ́n òǹrorò àti oníwà búburú ni ọkùnrin; ẹni ìdílé Kálẹ́bù ni òun jẹ́.

4. Dáfídì sì gbọ́ ní ihà pé Nábálì ń rẹ́ irun àgùntàn rẹ̀.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 25