Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 21:9-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Àlùfáà náà sì wí pé, “Idàn Gòláyátì ará Fílístínì tí ó pa ní àfonífojì Élà ní ń bẹ, wò ó, a fi aṣọ kan wé e lẹ́yìn Éródù; bí ìwọ yóò bá mú èyí, mú un; kò sì sí òmíràn níhìn mọ́ bí kò ṣe ọ̀kan náà.”Dáfídì sì wí pé, “Kò sí èyí tí ó dàbí rẹ̀ fún mi.”

10. Dáfídì sì dìde, o sì sá ni ọjọ́ náà níwájú Ṣọ́ọ̀lù, ó sì lọ sọ́dọ̀ Ákíṣì, ọba Gátì.

11. Àwọn ìránṣẹ́ Ákíṣì sì wí fún un pé, “Èyí há kọ́ ní Dáfídì ọba ilẹ̀ náà? Ǹjẹ́ wọn kò ha ti dárin ti wọ́n sì gbe orin nítorí rẹ̀, tí wọ́n sì jó pé,“ ‘Ṣọ́ọ̀lù pá ẹgbẹ̀rún tírẹ.Dáfídì sì pa ẹgbàarún tirẹ̀’?”

12. Dáfídì sì pa ọ̀rọ̀ wọ̀nyí í mọ́ ni ọkàn rẹ̀, ó sì bẹ̀rù Ákíṣì ọba Gátì gidigidi.

13. Òun sì pa ìṣe rẹ̀ dà níwájú wọn, ó sì sọ ara rẹ̀ di aṣiwèrè ní ọwọ́ wọn, ó sì ń fi ọwọ́ rẹ̀ ha ilẹ̀kùn ojú ọ̀nà, ó sì ń wá itọ́ sí irungbọ̀n rẹ̀.

14. Nígbà náà ni Ákíṣì wí fún àwọn ìrańṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wó o, nítorí kín ni ẹ̀yin ṣe mú un tọ̀ mí wá.

15. Mo há ni un fi aṣiwèrè ṣe? Tí ẹ̀yin fi mú èyí tọ̀ mí wá lati hú ìwà aṣiwèrè níwájú mi? Eléyìí yóò há wọ inú ilé mi?”

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 21