Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 16:21-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Dáfídì sì tọ Ṣọ́ọ̀lù lọ, ó sì dúró níwájú rẹ̀: òun sì fẹ́ ẹ gidigidi, Dáfídì sì wá di ẹni tí ń ru ìhámọ́ra rẹ̀.

22. Nígbà náà ni Ṣọ́ọ̀lù ránṣẹ́ sí Jésè, pé, “Jẹ́ kí Dáfídì dúró níwájú mi, nítorí tí ó wù mí.”

23. Ó sì ṣe, nígbà tí ẹ̀mi búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá bá dé sí Ṣọ́ọ̀lù, Dáfídì a sì fi ọwọ́ rẹ̀ kọrin lára dùùrù: a sì san fún Ṣọ́ọ̀lù, ara rẹ̀ a sì dá; ẹ̀mi búburú náà a sì fi sílẹ̀.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 16