Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 14:44-52 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

44. Ṣọ́ọ̀lù sì wí pé, “Kí Olúwa kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ sí mi, bí ìwọ kò bá kú.”

45. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wí fún Ṣọ́ọ̀lù pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí Jónátanì kú, ẹni tí ó ti mú ìgbàlà ńlá yìí wá fún Ísírẹ́lì? Kí a má rí í! Bí Olúwa ti wà, ọ̀kan nínú irun orí rẹ̀ kì yóò bọ́ sílẹ̀, nítorí tí ó ṣe èyí pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́.” Báyìí ni àwọn ènìyàn gba Jónátanì sílẹ̀, kò sì kú.

46. Nígbà náà ni Ṣọ́ọ̀lù sì dẹ́kun lílépa àwọn Fílístínì, àwọn Fílístínì sì padà sí ìlú wọn.

47. Lẹ́yìn ìgbà tí Ṣọ́ọ̀lù ti jọba lórí Ísírẹ́lì, ó sì bá gbogbo ọ̀tá wọn jà yíká: Móábù àti àwọn ọmọ Ámónì; Édómù, àti àwọn ọba Ṣọ́bà, àti àwọn Fílístínì. Ibikíbi tí ó bá kọjú sí, ó máa ń fi ìyà jẹ wọ́n.

48. Ó sì jà tagbáratagbára, ó ṣẹ́gun àwọn Ámálékì, ó sì ń gba Ísírẹ́lì sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tí ó ń kọlù wọ́n.

49. Àwọn ọmọ Sọ́ọ̀lù sì ni Jónátánì, Ísúì àti Málíkísúà. Orúkọ ọmọbìnrin rẹ̀ àgbà sì ni Mérábù àti orúkọ ọmọbìnrin rẹ̀ kékeré ni Míkálì.

50. Orúkọ ìyàwó rẹ̀ ní Áhínóámù ọmọbìnrin Áhímásì. Orúkọ olórí ogun rẹ̀ ni Ábínérì ọmọ Nérì arákùnrin baba Sọ́ọ̀lù.

51. Kíṣì baba Ṣọ́ọ̀lù àti Ábínérì baba Nérì sì jẹ́ ọmọ Ábíélì.

52. Ní gbogbo ọjọ́ Ṣọ́ọ̀lù, ogun náà sì gbóná sí àwọn Fílístínì, níbikíbi tí Ṣọ́ọ̀lù bá sì ti rí alágbára tàbí akíkanjú ọkùnrin, a sì mú u láti máa bá a ṣiṣẹ́.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 14