Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 14:21-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Àwọn Hébérù tí ó ti wà lọ́dọ̀ àwọn Fílístínì tẹ́lẹ̀, tí wọ́n sì ti gòkè tẹ̀lé wọn lọ sí àgọ́ wọn wá sọ́dọ̀ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tí wọ́n ti wà pẹ̀lú Ṣọ́ọ̀lù àti Jónátanì.

22. Nígbà tí gbogbo àwọn Ísírẹ́lì tí ó ti pa ara wọn mọ́ nínú òkè ńlá Éfúráímù gbọ́ pé àwọn Fílístínì sá, wọ́n darapọ̀ mọ́ ìjà náà ní ìlépa gbígbóná.

23. Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì gba Ísírẹ́lì ní ọjọ́ náà, ìjà náà sì rékọjá sí Bẹti-Áfénì.

24. Gbogbo ọkùnrin Ísírẹ́lì sì wà ní ìpọ́njú ńlá ní ọjọ́ náà, nítorí pé Ṣọ́ọ̀lù ti fi àwọn ènìyàn gégùn ún wí pé, “Ègbé ni fún ẹni tí ó jẹ oúnjẹ títí di alẹ́, títí èmi yóò fi gbẹ̀san mi lára àwọn ọ̀ta mi!” Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkankan nínú ọ̀wọ́ ogun náà tí ó fi ẹnu kan oúnjẹ.

25. Gbogbo àwọn ènìyàn sì wọ inú igbó, oyin sì wà lórí ilẹ̀ náà.

26. Nígbà tí wọ́n dé inú igbó náà, wọ́n sì rí oyin ń sun jáde, kò sí ẹni tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ kan ẹnu rẹ̀ ṣíbẹ̀, nítorí pé wọ́n bẹ̀rù ìfiré.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 14