Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 14:12-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Àwọn ọkùnrin ìlú olódi náà sì kígbe sí Jónátánì àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Ẹ gòkè tọ̀ wá wá àwa yóò sì kọ́ ọ yín ní ẹ̀kọ́.”Jónátánì sì wí fún ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Gòkè tọ̀ mí lẹ́yìn; Olúwa ti fi wọ́n lé Ísírẹ́lì lọ́wọ́.”

13. Jónátánì lo ọwọ́ àti ẹṣẹ̀ rẹ̀ láti fà gòkè pẹ̀lú ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ ní ọwọ́ ọ̀tún ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Àwọn Fílístínì sì ṣubú níwájú Jónátánì ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì tẹ̀lé e, ó sì ń pa lẹ́gbẹ̀ ẹ́ rẹ̀.

14. Ní ìkọlù èkíní yìí, Jónátanì àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì pa ogún ọkùnrin ní agbégbé tó tó ìwọ̀n ààbọ̀ sarè ilẹ̀.

15. Nígbà náà ni ìbẹ̀rù bojo bá àwọn ọmọ ogun; àwọn tí ó wà ní ibùdó àti ní pápá, àti àwọn tí ó wà ní ilé ìlú olódi àti àwọn tí ń kó ìkógun, ilẹ̀ sì mì. Ó jẹ́ ìbẹ̀rù tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.

16. Àwọn tí ó ń ṣọ́nà fún Sàúlù ní Gíbéà ti Bẹ́ńjámínì sì rí àwọn ọmọ ogun ń túká ní gbogbo ọ̀nà.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 14