Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Sámúẹ́lì 1:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọkùnrin kan wà, láti Rámátaímù-Sófímù, láti ìlú olókè Éfúráímù, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Elikánà, ọmọ Jéróhámù, ọmọ Élíhù, ọmọ Tóhù, ọmọ Súfù, ará Éfírátà.

2. Ó sì ní ìyàwó méjì: orúkọ wọn ni Hánà àti Pẹ̀nínà: Pẹ̀nínà ní ọmọ, ṣùgbọ́n Hánà kò ní.

3. Ní ọdọọdún, ọkùnrin yìí máa ń gòkè láti ìlú rẹ̀ láti lọ sìn àti láti ṣe ìrúbọ sí Olúwa alágbára jùlọ ní Ṣílò, níbi tí àwọn ọmọkùnrin Élì méjèèjì, Hófínì àti Fínéhásì ti jẹ́ àlùfáà Olúwa.

4. Nígbàkígbà tí ó bá kan Elikánà láti ṣe ìrúbọ, òun yóò bù lára ẹran fún aya rẹ̀ Pẹ̀nínà àti fún gbogbo àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin.

5. Ṣùgbọ́n ó máa ń pín ìlọ́po fun Hánà nítorí pé ó fẹ́ràn rẹ̀ àti pé Olúwa ti sé e nínú.

Ka pipe ipin 1 Sámúẹ́lì 1