Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 9:24-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Lẹ́yìn ìgbà tí ọmọbìnrin Fáráò ti gòkè láti ìlú Dáfídì wá sí ààfin tí Sólómónì kọ́ fún un, nígbà náà ni ó kọ́ Mílò.

25. Nígbà mẹ́ta lọ́dún ni Sólómónì ń rú ẹbọ ọrẹ sísun àti ẹbọ àlàáfíà lórí pẹpẹ tí ó tẹ́ fún Olúwa, ó sì sun tùràrí níwájú Olúwa pẹ̀lú wọn, bẹ́ẹ̀ ni ó parí ilé náà.

26. Sólómónì ọba sì tún ṣe òwò ọkọ̀ ní Esioni-Gébérì, tí ó wà ní ẹ̀bá Élátì ní Édómù, létí òkun pupa.

27. Hírámù sì rán àwọn ènìyàn rẹ̀, àwọn atukọ̀ tí ó mọ òkun, pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́ Sólómónì.

28. Wọ́n sì dé ófírì, wọ́n sì mú irínwó ó lé ogún (420) talẹ́ǹtì wúrà, tí wọ́n ti gbà wá fún Sólómónì ọba.

Ka pipe ipin 1 Ọba 9