Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 8:11-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Àwọn àlùfáà kò sì le ṣiṣẹ́ wọn nítorí àwọ̀sánmà náà, nítorí ògo Olúwa kún ilé náà.

12. Nígbà náà ni Sólómónì sì wí pé, “Olúwa ti wí pé, òun yóò máa gbé inú òkùnkùn biribiri;

13. Nítòótọ́ èmi ti kọ́ ilé kan fún ọ, ibi tí ìwọ yóò máa gbé títí láéláé.”

14. Nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Ísírẹ́lì sì dúró síbẹ̀, ọba sì yí ojú rẹ̀, ó sì bùkún fún wọn.

15. Nígbà náà ni ó wí pé:“Ìbùkún ni fún Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, ẹni tí ó ti fi ọwọ́ ara rẹ̀ mú ìlérí tí ó fi ẹnu rẹ̀ sọ fún Dáfídì bàbá mi ṣẹ. Nítorí tí ó wí pé,

16. ‘Láti ọjọ́ tí èmi ti mú àwọn ènìyàn mi Ísírẹ́lì jáde kúrò ní Éjíbítì, èmi kò tí ì yan ìlú kan nínú gbogbo ẹ̀yà Ísírẹ́lì láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi láti wà níbẹ̀, ṣùgbọ́n èmi ti yan Dáfídì láti ṣàkóso àwọn Ísírẹ́lì ènìyàn mi.’

17. “Dáfídì baba mi sì ní i lọ́kàn láti kọ́ ilé kan fún orúkọ Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì.

18. Ṣùgbọ́n Olúwa sì wí fún Dáfídì bàbá mi pé, ‘Nítorí tí ó wà ní ọkàn rẹ láti kọ́ ilé kan fún orúkọ mi, ó dára láti ní èyí ní ọkàn rẹ.

Ka pipe ipin 1 Ọba 8