Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 4:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Sólómónì ọba sì jọba lórí gbogbo Ísírẹ́lì.

2. Àwọn wọ̀nyí sì ni ìjòyè rẹ̀:Ásáríyà ọmọ Ṣádókù àlùfáà:

3. Élíhóréfù àti Áhíjà àwọn ọmọ Ṣísánì akọ̀wé;Jèhósáfátì ọmọ Áhílúdì ni akọ̀wé ìlú;

4. Bénáyà ọmọ Jéhóíádà ni olórí ogun;Sádókù àti Ábíátarì ni àwọn àlùfáà;

5. Ásáríyà ọmọ Nátanì ni olórí àwọn agbègbè;Sóbúdù ọmọ Nátanì, àlùfáà àti olùgba ọba ní ìmọ̀ràn;

6. Áhísárì ni olùtọ́jú ààfin;Ádónírámù ọmọ Ábídà ni ó ń ṣe olórí iṣẹ́-ìlú

7. Sólómónì sì tún ní ìjòyè méjìlá lórí gbogbo agbégbé Ísírẹ́lì, tí wọ́n ń pèsè oúnjẹ fún ọba àti agbo ilé rẹ̀. Olúkúlùkù ní láti pèsè fún oṣù kan ní ọdún.

8. Orúkọ wọn ni wọ̀nyí:Bénhúrì ní ìlú olókè Éfúráímù.

Ka pipe ipin 1 Ọba 4