Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 15:25-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Nádábù ọmọ Jéróbóámù sì jọba lórí Ísírẹ́lì ní ọdún kejì Áṣà ọba Júdà, ó sì jọba lórí Ísírẹ́lì ní ọdún méjì.

26. Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà bàbá rẹ̀ àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó mú Ísírẹ́lì dá.

27. Bááṣà ọmọ Áhíjà ti ilé Ísákárì sì dìtẹ̀ sí i, Bááṣà sì kọlù ú ní Gíbétónì, ìlú àwọn ará Fílístínì, nígbà tí Nádábù àti gbogbo Ísírẹ́lì dó ti Gíbétónì.

28. Bááṣà sì pa Nádábù ní ọdún kẹta Áṣà ọba Júdà, ó sì jọba ní ipò rẹ̀.

29. Ó sì ṣe, bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jọba ó pa gbogbo ilé Jéróbóámù, kò sì ku ẹnìkan tí ń mí fún Jéróbóámù, ṣùgbọ́n ó run gbogbo wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ó sọ nípa ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ Áhíjà ará Ṣílò:

30. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jéróbóámù ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Ísírẹ́lì ṣẹ̀, àti nítorí tí ó ti mú Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì bínú.

31. Níti ìyókù ìṣe Nádábù àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Ísírẹ́lì?

32. Ogun sì wà láàrin Áṣà àti Bááṣà ọba Ísírẹ́lì ní gbogbo ọjọ́ wọn.

Ka pipe ipin 1 Ọba 15