Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 12:28-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

28. Lẹ́yìn tí ó ti gba ìmọ̀ràn, ọba sì yá ẹgbọ̀rọ̀ màlúù wúrà méjì. Ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ó ti pọ̀jù fún yín láti máa gòkè lọ sí Jérúsálẹ́mù. Àwọn Ọlọ́run yín nìyìí, Ísírẹ́lì, tí ó mú yín láti ilẹ̀ Éjíbítì wá.”

29. Ó sì gbé ọ̀kan kalẹ̀ ní Bétélì, àti èkejì ní Dánì.

30. Nǹkan yìí sì di ẹ̀ṣẹ̀; àwọn ènìyàn sì lọ títí dé Dánì láti sin èyí tí ó wà níbẹ̀.

31. Jéróbóámù sì kọ́ ojúbọ sórí ibi gíga, ó sì yan àwọn àlùfáà láti inú àwọn ènìyàn bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kì í ṣe inú àwọn ọmọ Léfì.

32. Ó sì dá àṣè sílẹ̀ ní ọjọ́ kẹẹ̀dógún oṣù kẹjọ gẹ́gẹ́ bí àṣè tí ó wà ní Júdà, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ. Ó ṣe èyí ní Bétélì, ó rú ẹbọ sí àwọn ọmọ màlúù tí ó ṣe. Ó sì fi àwọn àlùfáà sí ibi gíga tí ó ti ṣe sí Bétélì.

33. Ní ọjọ́ kẹẹ̀dógún oṣù kẹjọ, oṣù tí ó rò ní ọkàn ara rẹ̀, ó sì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí ó kọ́ ní Bétélì. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dá àsè sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ó sì gun orí pẹpẹ náà lọ láti rú ẹbọ.

Ka pipe ipin 1 Ọba 12