Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Ọba 12:1-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Réhóbóámù sì lọ sí Ṣékémù, nítorí gbogbo Ísírẹ́lì ti lọ síbẹ̀ láti fi í jẹ ọba.

2. Nígbà tí Jéróbóámù ọmọ Nébátì, tí ó wà ní Éjíbítì síbẹ̀ gbọ́, nítorí tí ó ti sá kúrò níwájú Sólómónì ọba, ó sì wà ní Éjíbítì.

3. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ránṣẹ́ sí Jéróbóámù, òun àti gbogbo ìjọ Ísírẹ́lì sì lọ sọ́dọ̀ Réhóbóámù, wọ́n sì wí fún un pé:

4. “Baba rẹ sọ àjàgà wa di wúwo, ṣùgbọ́n nísinsìnyí, mú kí ìsìn baba rẹ̀ tí ó le, àti àjàgà rẹ̀ tí ó wúwo, tí ó fi sí wa ní ọrùn kí ó fẹ́rẹ̀ díẹ̀, àwa yóò sì sìn ọ́.”

5. Réhóbóámù sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ ná títí di ọjọ́ mẹ́ta, nígbà náà ni kí ẹ padà tọ̀ mí wá.” Àwọn ènìyàn náà sì lọ.

6. Nígbà náà ni Réhóbóámù ọba fi ọ̀rọ̀ lọ àwọn àgbààgbà tí ń dúró níwájú Sólómónì baba rẹ̀ nígbà tí ó wà láàyè. Ó sì béèrè pé, “Ìmọ̀ràn wo ni ẹ̀yin yóò gbà mí láti dá àwọn ènìyàn wọ̀nyí lóhùn?”

7. Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Bí ìwọ yóò bá jẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí lónìí, kí o sì sìn wọ́n, àti kí o sì sọ ọ̀rọ̀ rere sí wọn nígbà tí ìwọ bá ń dá wọn lóhùn, wọn yóò má a ṣe ìránṣẹ́ rẹ títí láé.”

8. Ṣùgbọ́n Réhóbóámù kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbààgbà fún un, ó sì fi ọ̀rọ̀ náà lọ àwọn ọmọdé tí wọ́n dàgbà pẹ̀lú rẹ̀, tí wọ́n sì ń sìn ín.

9. Ó sì bi wọ́n pé, “Kí ni ìmọ̀ràn yín? Báwo ni a ó ṣe dá àwọn ènìyàn yí lóhùn, tí wọ́n wí fún mi pé, Ṣé kí àjàgà tí baba rẹ fi sí wa lọ́rùn kí ó fúyẹ́ díẹ̀?”

10. Àwọn ọmọdé tí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Sọ fún àwọn ènìyàn tí wọ́n wí fún ọ pé, ‘Baba rẹ̀ mú kí àjàgà wa wúwo ṣùgbọ́n ìwọ mú kí ó fúyẹ́ díẹ̀ fún wa’; sọ fún wọn pé, ìka ọwọ́ mi kékeré nípọn ju ẹ̀gbẹ́ baba mi lọ.

11. Baba mi ti gbé àjàgà wúwo lé e yín; Èmi yóò sì fi kún àjàgà yín. Baba mi ti fi pàsán nà yín; Èmi yóò fi àkéekèe nà yín.”

12. Jéróbóámù àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wá sọ́dọ̀ Réhóbóámù ní ọjọ́ kẹta, gẹ́gẹ́ bí ọba ti wí pé, “Ẹ padà tọ̀ mí wá ní ọjọ́ kẹta.”

13. Ọba sì fi ohùn líle dá àwọn ènìyàn lóhùn, ó sì kọ ìmọ̀ràn tí àwọn àgbààgbà fún un,

14. Ó sì tẹ̀lé ìmọ̀ràn àwọn ọmọdé, ó sì wí pé, “Baba mí sọ àjàgà yín di wúwo; Èmi yóò sì jẹ́ kí ó wúwo sí i; Baba mi fi pàsán nà yín; Èmi yóò fí àkéekèe nà yín.”

15. Bẹ́ẹ̀ ni ọba kò sì fi etí sí ti àwọn ènìyàn, nítorí tí ọ̀ràn náà ti ọwọ́ Olúwa wá láti mú ọ̀rọ̀ tí ó sọ fún Jéróbóámù ọmọ Nébátì láti ẹnu Áhíjà ará Ṣílò ṣẹ.

16. Nígbà tí gbogbo Ísírẹ́lì rí i pé ọba kọ̀ láti gbọ́ ti àwọn, wọ́n sì dá ọba lóhùn pé:ìpín wo ni àwa ní nínú Dáfídì,Ìní wo ni àwa ní nínú ọmọ Jésè?Padà sí àgọ́ rẹ, ìwọ Ísírẹ́lì!Bojútó ilé ara rẹ, ìwọ Dáfídì!Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Ísírẹ́lì padà sí ilé wọn.

Ka pipe ipin 1 Ọba 12