Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 9:33-44 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

33. Àwọn tí wọ́n jẹ́ ọkùnrin, olórí àwọn ìdílé Léfì dúró nínú àgọ́ ilé Olúwa, wọn kò sì se lára isẹ́ ìsìn yòókù nítorí wọ́n ń se isẹ́ náà lọ́sán, lóru.

34. Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn Léfì, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti se kọ lẹ́sẹsẹ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jérúsálẹ́mù.

35. Jélíélì baba Gíbíónì ń gbé ní Gíbíónì.Orúkọ ìyàwó Rẹ̀ a má a jẹ́ Mákà,

36. Pẹ̀lú àkọ́bí ọmọkùnrin Rẹ̀ jẹ́ Ábídónì, tí wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Ṣúrì, Kíṣì Bálì, Nérì, Nádábù.

37. Gédórì, Áhíò, Sékaráyà àti Míkílótì.

38. Míkílótì jẹ́ baba Ṣíméámì, àwọn náà ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jérúsálẹ́mù.

39. Nérì jẹ́ baba Kíṣì, Kíṣì baba a Ṣọ́ọ̀lù, àti Ṣọ́ọ̀lù baba a Jónátanì, àti Málíkíṣuà, Ábínádábù àti Éṣí-Bálì.

40. Ọmọ Jónátanì:Méríbú Bálì, tí ó jẹ́ baba a Míkà:

41. Àwọn ọmọ Míkà:Pítónì. Mélékì, Táhíréà àti Áhásì.

42. Áhásì jẹ́ baba Jádà, Jádà jẹ́ baba Álémétì, Aṣimáfétì, Ṣímírì, sì Ṣímírì jẹ́ baba Móṣà.

43. Móṣà jẹ́ baba Bínéà; Réfáíà jẹ́ ọmọ Rẹ̀, Éléásà ọmọ Rẹ̀ àti Áṣélì ọmọ Rẹ̀.

44. Áṣélì ní ọmọ mẹ́fà, pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn:Áṣíríkámù, Bókérù, Ísímáélì Ṣéáríà, Óbádíà àti Hánánì Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Áṣélì.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 9