1. Bẹ́ńjámínì jẹ́ bàbá Bélà àkọ́bí Rẹ̀,Áṣíbélì ọmọkùnrin ni ẹ̀ẹ̀kejì, Áhárá ẹ̀ẹ̀kẹ́ta,
2. Nóhà ẹ̀ẹ̀kẹrin àti Ráfà ẹ̀ẹ̀karùnún.
3. Àwọn ọmọ Bélà jẹ́:Ádárì, Gérà, Ábíhúdì,
4. Ábísúà, Námánì, Áhóà,
5. Gérà, Ṣéfúfánì àti Húrámù.
6. Wọ̀nyí ni àwọn ìran ọmọ Éhúdì, tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé tí ó ń gbé ní Gébà tí a sì lé kúrò lọ sí Mánáhátì:
7. Námánì Áhíjà àti Gérà, tí ó lé wọn kúrò ní ìlú, àti tí ó sì jẹ́ baba Úṣà àti Áhíhúdù.
8. A bí àwọn ọmọkùnrin fún Ṣáháráímù ní Móábù lẹ́yìn tí ó ti kọ àwọn ìyàwó Rẹ̀ sílẹ̀, Húṣímù àti Báárà.
9. Nípaṣẹ̀ ìyàwó Rẹ̀ Hódéṣì ó ní Jóbábù ṣíbíà, Méṣà, Málíkámà,
10. Jéúṣì Ṣákíà àti Mírímà. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin Rẹ̀, olórí àwọn ìdílé.