Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 7:8-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Àwọn ọmọ Békérì:Ṣémíráhì, Jóáṣì, Élíásérì, Élíóénáì, omírì, Jeremótù Ábíjà, Ánátótì àti Álémétì Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ ọmọ Békérì

9. Ìtàn ìdílé wọn láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn tí a kọ lẹ́sẹsẹ jẹ́ ti àwọn olórí ìdílé àti ẹgbẹ̀rún-ní ọ̀nà ogún-ó-lé nígba (20,200) Ọkùnrin alágbára

10. Ọmọ Jédíáélì:Bílíhánì.Àwọn ọmọ Bílíhánì:Jéúṣì Bẹ́ńjámínì, Éhúdì, Kénánà Ṣétanì, Tárí-Ṣíṣì àti Áhísáhárì.

11. Gbogbo àwọn ọmọ Jédíádì jẹ́ olórí ìdátan Àwọn ẹgbẹ̀rúnmẹ́tadínlógún-ó-lé-nígba akọni ọkùnrin ni ó ti ṣetan láti jáde lọ sí ogun.

12. Àwọn ará Ṣúpímè àti Húpímù jẹ́ àwọn atẹ̀lé fún Írì, àwọn ìran ọmọ Áhérì.

13. Àwọn ọmọ Náfítalì:Jáhíṣíẹ́lì, Gúnì, Jésérì àti Ṣílémù—ọmọ Rẹ̀ nípa Bílíhà.

14. Àwọn ìran ọmọ Mánásè:Ásíríélì jẹ́ ìran ọmọ Rẹ̀ nípa sẹ̀ àlè Rẹ̀ ará Árámù ó bí Mákírì baba Gílíádì.

15. Mákírì sì mú ìyàwó láti àárin àwọn ará Hípímù àti Ṣúpímù. Orúkọ arábìnrin Rẹ̀ a má a jẹ́ Máákà.Orúkọ ìran ọmọ mìíràn a má a jẹ́ Ṣélóféhádì, tí ó ní àwọn ọmọbìnrin nìkan ṣoṣo.

16. Máákà, ìyàwó Mákírì bí ọmọkùnrin kan. Ó sì sọ orúkọ Rẹ̀ ní Pérésì. Ó sì pe arákùnrin Rẹ̀ ní Ṣéréṣì, àwọn ọmọ Rẹ̀ sì ní Úlámù àti Rákémù.

17. Ọmọ Úlámù:Bédánì.Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gílíádì ọmọ Mákírì, ọmọ Mánásè.

18. Arábìnrin Rẹ̀. Hámólékétì bí Ṣíhódì, Ábíésérì àti Máhíláhì.

19. Àwọn ọmọ Ṣémídà sì jẹ́:Áhíánì, Ṣékémù, Líkì àti Áníámù.

20. Àwọn ìran ọmọ Éfíráímù:Ṣútéláhì, Bérédì ọmọkùnrin Rẹ̀,Táhátì ọmọ Rẹ̀, Éléádáhì ọmọ Rẹ̀.

21. Táhátì ọmọ Rẹ̀ Ṣábádì ọmọ, Rẹ̀,àti Ṣútéláhì ọmọ Rẹ̀.Éṣérì àti Éléádì ni a pá nípaṣẹ̀ àwọn ọkùnrin bíbí ìbílẹ̀ Gátì Nígbà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ fi agbára mú ohun ọ̀sìn wọn

22. Éfíráímù baba wọn sọ̀fọ̀ fún wọn ní ọjọ́ púpọ̀, àwọn ìbátan Rẹ̀ wá láti tù ú nínú.

23. Nígbà náà, ó sùn pẹ̀lú, ìyàwó Rẹ̀, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin kan. Ó sì sọ ọ́ ní Béríà nítorí òfò ti wà nínú ìdílé náà.

24. Ọmọbìnrin Rẹ̀ sì jẹ́ Ṣárà, ẹni tí ó kọ́ ìsàlẹ̀ àti òkè Bétí-Hórónì àti Úṣénì sérà pẹ̀lú.

25. Réfà jẹ́ ọmọ Rẹ̀, Rẹ́sẹ́fì ọmọ Rẹ̀,Télà ọmọ Rẹ̀, Táhánì ọmọ Rẹ̀,

26. Ládánì ọmọ Rẹ̀ Ámíhúdì ọmọ Rẹ̀,Élíṣámà ọmọ Rẹ̀,

27. Núnì ọmọ Rẹ̀àti Jóṣúà ọmọ Rẹ̀.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 7