Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 7:29-40 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Lẹ́gbẹ̀ ìpínlẹ̀ ti Mánásè ni Bétí ṣánì, Tánákì, Mógídò àti Dórì lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ìletò Rẹ̀. Àwọn ìran ọmọ Jóṣẹ́fù ọmọ Ísírẹ́lì ń gbé nínú ìlú wọ̀nyí.

30. Àwọn ọmọ Ásérì:Ímíná, Ísúa, Ísúáì àti Béríá. Arábìnrin wọn sì jẹ́ Ṣérà.

31. Àwọn ọmọ Béríá:Hébérì àti Málíkíélì, tí ó jẹ́ baba Bírísáítì.

32. Hébérì jẹ́ baba Jáfílétì, Ṣómérì àti Hótamì àti ti arábìnrin wọn Ṣúà.

33. Àwọn ọmọ Jáfílétì:Pásákì, Bímíhátì àti Ásífátì.Wọ̀n yí ni àwọn ọmọ Jáfílétì.

34. Àwọn ọmọ Ṣómérì:Áhì, Rógà, Jáhúbà àti Árámù.

35. Àwọn ọmọ arákùnrin Rẹ̀ HélémùṢófà, Ímínà, Ṣélésì àti Ámálì.

36. Àwọn ọmọ Ṣófáhì:Ṣúà, Háníférì, Ṣúálì, Bérì Ímírà.

37. Béṣérì Hódì, Ṣámà, Ṣílísà, Ítíránì àti Bérà.

38. Àwọn ọmọ Jétérì:Jéfúnè Písífà àti Árà.

39. Àwọn ọmọ Úlà:Árà Háníélì àti Résíà.

40. Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ ìran ọmọ Áṣérì olórí ìdílé, àwọn okùnrin tí a yàn àwọn ògbóyà jagunjagun àti àwọn adarí tí ó dúró sinsin. Iye àwọn ọkùnrin tí ó setan fún ogun, gẹ́gẹ́ bí à ti se kọ ọ́ lẹ́sẹsẹ nínú ìtàn ìdílé wọn láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 7