Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 5:5-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Míkà ọmọ Rẹ̀,Réáíà ọmọ Rẹ̀, Báálì ọmọ Rẹ̀.

6. Béérà ọmọ Rẹ̀, tí Tígílátì-pílínésérì ọba Ásíríà kó ní ìgbékùn lọ: ìjòyè àwọn ọmọ Rúbẹ́nì ni òun jẹ́.

7. Àti àwọn arákùnrin Rẹ̀ nípa ìdílé wọn, nígbà tí a ń ka ìtàn ìdílé ìran wọn:Jélíélì àti Ṣékáríà ni olórí.

8. Àti Bélà ọmọ Ásásì ọmọ Ṣémà, ọmọ Jóẹ́lì tí ń gbé Áróérì àní títí dé Nébò àti Baaliméónì.

9. Àti níhà àríwá, o tẹ̀dó lọ títí dé àti wọ ihà láti odo Yúfúrátè; nítorí tí ẹran ọ̀sìn wọn pọ̀ si i ní ilẹ̀ Gílíádì.

10. Àti ní ọjọ́ Ṣọ́ọ̀lù, wọ́n bá àwọn ọmọ Hágárì jagun, ẹni tí ó ṣubú nípa ọwọ́ wọn; wọ́n sì ń gbé inú àgọ́ wọn ní gbogbo ilẹ̀ àríwá Gílíádì.

11. Àti àwọn ọmọ Gádì ń gbé ọ̀kánkán wọn, ní ilẹ̀ Básánì títí dé Sálíkà:

12. Jóẹ́lì olórí, Ṣáfámù ìran ọmọ, Jánáì, àti Ṣáfátì ni Básánì,

13. Àti àwọn arákùnrin wọn ti ilẹ̀ àwọn baba wọn ní:Míkáélì, Mésúlímù Ṣébà, Jóráì, Jákánì, Ṣíà àti Hébérì méje.

14. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ábíháílì, ọmọ Húrì, ọmọ Járóà, ọmọ Gílíádì, ọmọ Míkàẹ́lì, ọmọ Jésíháì, ọmọ Jádò ọmọ Búsì.

15. Áhì, ọmọ Ábídélì, ọmọ Gúnì, olórí ilé àwọn baba wọn.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 5