Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 3:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Àwọn wọ̀nyí sì ni ọmọ Dáfídì tí a bí fún un ní Hébírónì:Àkọ́bí sì ni Ámínónì ọmọ Áhínóámù ti Jésírẹ́lì;èkejì sì ni Dáníẹ́lì ọmọ Ábígáílì ará Kárímélì;

2. Ẹ̀kẹta sì ni Ábúsálómù ọmọ Mákà ọmọbìnrin ti Táímáì ọba Gésúrì;ẹ̀kẹrin sì ni Àdóníjà ọmọ Hágítì;

3. Ẹ̀kárùnún ni Ṣéfátíyà ọmọ Ábítalì;àti ẹ̀kẹfà, Ítíréàmù, láti ọ̀dọ̀ ìyàwó Rẹ̀ Égílà.

4. Ẹ̀kẹfà ni a bí fún Dáfídì ni Hébúrónì, níbi tí ó ti jẹ ọba fún ọdún méje àti oṣù mẹ́fà.Dáfídì sì jẹ ọba ní Jérúsálẹ́mù fún ọdún mẹ́talélọ́gbọ̀n (33).

5. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ wẹ́wẹ́ tí a bí fún un:Ṣámúyà, Ṣóbábù, Náhátì àti Sólómónì. Àwọn mẹ́rin wọ̀nyí sì ni a bí láti ọ̀dọ̀ Bátíṣébà ọmọbìnrin Ámíélì.

6. Íbíhárì sì wà pẹ̀lú, Élíṣúà, Élífélétì,

7. Nógà, Néfégì, Táfíà,

8. Élísámù, Élíádà àti Élífétélì mẹ́sàn án ni wọ́n.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 3