Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 29:13-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Nísinsìn yìí, Ọlọ́run wa, àwa fi ọpẹ́ fún Ọ,a sì fi ìyìn fún orúkọ Rẹ̀ tí ó lógo.

14. “Ṣùgbọ́n Ta ni èmi, àti ta ni àwọn ènìyàn mi, tí a fi lè fi sílẹ̀ tinútínú bí irú èyí? Gbogbo nǹkan wá láti ọ̀dọ̀ rẹ, àwa sì ti fífún ọ láti ara ohun tí ó wá láti ọwọ́ rẹ.

15. Àwa jẹ́ àjèjì àti àlejò ní ojú rẹ gẹ́gẹ́ bí baba ńlá a wa, àwọn ọjọ́ wa lórí ilẹ̀ ayé rí bí òjìji láìsí ìrètí.

16. Olúwa Ọlọ́run wa tí fi gbogbo pípọ̀ yìí tí àwa ti pèṣè fún kíkọ́ ilé Olúwa fun orúkọ, mímọ́ Rẹ̀, ó wá láti ọwọ́ ọ̀ rẹ, gbogbo Rẹ̀ sì jẹ́ tirẹ̀.

17. Èmi mọ̀ Ọlọ́run mi, wí pé ìwọ̀ dán ọkàn wò, ó sì tẹ́ ọ lọ́rùn pẹ̀lú òtítọ́ inú. Gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni èmi ti fi sílẹ̀ pẹ̀lú tìfẹ́tìfẹ́ pẹ̀lú òtítọ́. Nísinsìn yìí èmi ti ríi pẹ̀lú ayọ̀ bí àwọn ènìyàn yìí tí ó wà níbí ti fi fún ọ pẹ̀lú tìfẹ́tìfẹ́.

18. Olúwa Ọlọ́run àwọn baba a wa Ábúráhámù, Ísákì àti Ísírẹ́lì pa ìfẹ́ yìí mọ́ ninú ọkàn àwọn ènìyàn rẹ títí láé pẹ̀lú pípa ọkàn mọ́ lóòtọ́ sí ọ.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 29