Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 29:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà náà, ọba Dáfídì sọ fún gbogbo àpéjọ pé: “Ọmọ mi Sólomónì, èyí tí Ọlọ́run ti yàn, ṣì kéré ó sì jẹ́ aláìmòye. Iṣẹ́ náà tóbi, nítorí ìkọ́lé bí ti ààfin kì í ṣe fún ènìyàn ṣùgbọ́n fún Olúwa Ọlọ́run.

2. Pẹ̀lu gbogbo ìrànlọ́wọ́ mi èmi ti pèsè fún ilé Ọlọ́run mi wúrà fún iṣẹ́ wúrà, fàdákà fún ti fàdákà, òjíá fún ti òjíá, irin fún ti irin àti igi fún ti igi àti òkúta oníyebíye fún títọ́ Rẹ̀, (túríkúóṣè) òkúta lóríṣíríṣí, àmọ̀ àti oríṣìíríṣìí ẹ̀yà òkúta àti òkuta dáradára kan gbogbo wọ̀nyí ní iye púpọ̀.

3. Yàtọ̀ fún èyí, nínú ìfọkànsìn mi sí ilé Ọlọ́run mi, èmí fi ìṣúra mi tìkalára mí ti wúrà àti fàdákà fún ilé Ọlọ́run mi, jù gbogbo Rẹ̀ lọ, èmi ti pèṣè fún ilé mímọ́ ti Olúwa yìí:

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 29