Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 23:10-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Àti ọmọ Ṣímélì:Jáhátì, Ṣísà, Jéúsì àti Béríà.Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Ṣíméhì mẹ́rin ni gbogbo wọn.

11. Jáhátì sì ni alákọ́kọ́ Ṣísà sì ni ẹlẹ́kejì, ṣùgbọ́n Jéúsì àti Béríà kò ní àwọn ọmọ púpọ̀; Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ka ara wọn sí ìdílé kan pẹ̀lú ìfilé lọ́wọ́ kan.

12. Àwọn ọmọ kóhátì:Ámírámù, Ísárì, Hébúrónì àti Usíélì mẹ́rin ni gbogbo wọn.

13. Àwọn ọmọ Ámírámù.Árónì àti Móṣè.A sì ya Árónì sọ́tọ̀ òun àti àwọn ọmọ Rẹ̀ títí láéláé, láti kọjú sí ohun mímọ́ jùlọ, láti fi rúbọ sísun níwájú Olúwa, láti máa ṣe òjísẹ́ níwájú Rẹ̀ àti láti kéde ìbùkún ní orúkọ Rẹ̀ títí láéláé.

14. Àwọn ọmọ Mósè ènìyàn Ọlọ́run ni wọ́n kà gẹ́gẹ́ bí apákan ẹ̀yà Léfì.

15. Àwọn ọmọ Mósè;Gérísónì àti Élíásérì.

16. Àwọn ọmọ GérísónìṢúbáélì sì ni alákọ́kọ́.

17. Àwọn ọmọ Élíásérì:Réhábíà sì ni ẹni àkọ́kọ́.Élíásérì kò sì tún ní ọmọ mìíràn, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Réhábíà wọ́n sì pọ̀ níye.

18. Àwọn ọmọ Ísárì:Ṣélómítì sì ni ẹni àkọ́kọ́.

19. Àwọn ọmọ Hérónì:Jéríyà sì ni ẹni àkọ́kọ́, Ámáríyà sì ni ẹni ẹ̀ẹ̀kejì, Jáhásíélì sì ni ẹ̀ẹ̀kẹta àti Jékáméámù ẹ̀ẹ̀kẹrin.

20. Àwọn ọmọ Húsíélì:Míkà ni àkọ́kọ́ àti Íṣíà ẹ̀ẹ̀kejì.

21. Àwọn ọmọ Mérárì:Máhílì àti Músì.Àwọn ọmọ Máhílì:Élíásárì àti Kísì.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 23