Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 21:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Sátanì sì ru ọkàn Dáfídì sókè láti ka iye Ísírẹ́lì.

2. Bẹ́ẹ̀ ni Dáfídì sì wí fún Jóábù àti àwọn olórí ti àwọn ọ̀wọ́ ọmọ ogun, Lọ kí o lọ ka iye àwọn ọmọ Ísírẹ́lì láti Béríṣébà títí dé Dánì. Kí o sì padà wá sọ fún mi kí èmi kí ó le mọ iye tí wọ́n jẹ́.

3. Ṣùgbọ́n Jóábù dá a lóhùn pé Kí Olúwa pọ̀ sí ní ìgbà ọgọ́rùn ún ju ti tẹ́lẹ̀ lọ Olúwa ọba mi, sé gbogbo wọn kì í ṣe ìránṣẹ́ Olúwa ni? Kí ni ó dé tí Olúwa mi ṣe fẹ́ ṣèyí? Kí ni ó de tí yóò fi mú Ísírẹ́lì jẹ̀bi?

4. Ọ̀rọ̀ ọba, bí ó ti wù kí ó rí, borí tí Jóábù. Bẹ́ẹ̀ ni Jóábù kúrò ó sì jáde lọ sí Jérúsálẹ́mù.

5. Jóábù sì sọ iye tí àwọn ajagun ọkùnrin náà jẹ́ fún Dáfídì. Ní gbogbo Ísírẹ́lì, ó sì jásí ẹgbẹ̀rún ẹgbẹ̀rún àti ọ̀kẹ́ márùn-ún ènìyàn (Mílíọnù kan àti ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà ọgọ́rùn-ún) tí ó lè mú idà àti pẹ̀lú ọ̀kẹ́ mẹ́talélógún lé ẹgbàrún ní Júdà.

6. Ṣùgbọ́n Jóábù kó àwọn Léfì àti Bẹ́ńjámínì mọ́ iye wọn, nítorí àsẹ ọba jẹ́ ìríra fún un.

7. Àṣẹ yìí pẹ̀lú sì jẹ́ búburú lójú Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni ó sì díyàjẹ Ísírẹ́lì.

8. Nígbà náà Dáfídì sọ fún Ọlọ́run pé, Èmi ti dẹ́ṣẹ̀ gidìgidì nípa ṣíṣe èyí. Nísinsin yìí, èmi bẹ̀ ọ́, mú ìjẹ̀bi àwọn ìránṣẹ́ rẹ kúrò. Èmi ti hùwà òmùgọ̀ gidigidi.

9. Olúwa sì fi fún Gádì, aríran Dáfídì pé.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 21