Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 13:10-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Ìbínú Olúwa, sì ru sí Úsà, ó sì lùú bolẹ̀ nítorí o ti fi ọwọ́ Rẹ̀ lórí Àpótí ẹ̀rí. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì kú síbẹ̀ níwájú Ọlọ́run.

11. Nígbà náà Dáfídì sì bínú nítorí ìbínú Olúwa ké jáde lórí Úsá, àti títí di òní, wọ́n sì ń pe ibẹ̀ ní péresì-Ùsà.

12. Dáfídì sì bẹ̀rù Ọlọ́run ní ọjọ́ náà, ó sì bèèrè pé, Báwo ni èmi náà ó ṣe gbé àpótí ẹ̀rí Olórun sí ọ̀dọ̀ mi?

13. Kò gbé àpótí ẹ̀rí náà wá sí ọ̀dọ̀ ará Rẹ̀ ní ìlú ti Dáfídì dípò èyí, ó sì gbé e sí ẹ̀gbé, sí ilé Obedi-Édómù ará Gítì.

14. Àpótí ẹ̀rí Olúwa sì wà lọ́dọ̀ àwon ará ilé Obedi-Édómù ní ilé Rẹ̀ fún oṣù mẹ́ta, Olúwa sì bùkún agbo ilé àti gbogbo ohun tí ó ní.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 13