45. Nígbà tí Jóbábù sì kú, Húṣámù láti ilẹ̀ àwọn ará Témánì sì jẹ ọba ní ipò Rẹ̀.
46. Nígbà tí Húṣámù sì kú, Hádádì ọmọ Bédádì, ẹni tí ó kọlu Mídíánì ní agbégbé Móábù, ó sì jẹ ọba ní ipò Rẹ̀. Orúkọ ìlú Rẹ̀ sì ni Áfítì.
47. Nígbà tí Hádádì sì kú, Ṣámílà láti Másírékà, ó sì jọba ní ipò Rẹ̀
48. Nígbà tí Ṣámílà sì kú, Ṣáúlì láti Réhóbótì lórí odò sì jẹ ọba ní ipò Rẹ̀
49. Nígbà tí Ṣáúlì sì kú, Báli-hánánì, ọmọ Ákíbórì sì jẹ ọba ní ipò Rẹ̀.
50. Nígbà tí Báli-hánánì sì kú, Hádádì sì di ọba nípò Rẹ̀. Orúkọ ìlú Rẹ̀ sì ni Páì; àti orúkọ ìyàwó sì ni Méhélábélì ọmọbìnrin Métírédì, ọmọbìnrin Mésíhábù.
51. Hádádì sì kú pẹ̀lú.Àwọn olórí Édómù ni:Tímínà, Álífà, Jététì
52. Óhólíbámà, Élà, Pínónì.