Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kíróníkà 1:45-52 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

45. Nígbà tí Jóbábù sì kú, Húṣámù láti ilẹ̀ àwọn ará Témánì sì jẹ ọba ní ipò Rẹ̀.

46. Nígbà tí Húṣámù sì kú, Hádádì ọmọ Bédádì, ẹni tí ó kọlu Mídíánì ní agbégbé Móábù, ó sì jẹ ọba ní ipò Rẹ̀. Orúkọ ìlú Rẹ̀ sì ni Áfítì.

47. Nígbà tí Hádádì sì kú, Ṣámílà láti Másírékà, ó sì jọba ní ipò Rẹ̀

48. Nígbà tí Ṣámílà sì kú, Ṣáúlì láti Réhóbótì lórí odò sì jẹ ọba ní ipò Rẹ̀

49. Nígbà tí Ṣáúlì sì kú, Báli-hánánì, ọmọ Ákíbórì sì jẹ ọba ní ipò Rẹ̀.

50. Nígbà tí Báli-hánánì sì kú, Hádádì sì di ọba nípò Rẹ̀. Orúkọ ìlú Rẹ̀ sì ni Páì; àti orúkọ ìyàwó sì ni Méhélábélì ọmọbìnrin Métírédì, ọmọbìnrin Mésíhábù.

51. Hádádì sì kú pẹ̀lú.Àwọn olórí Édómù ni:Tímínà, Álífà, Jététì

52. Óhólíbámà, Élà, Pínónì.

Ka pipe ipin 1 Kíróníkà 1