9. Lójijì, a ó ké eniyan burúkú lulẹ̀;ìjì ibinu Ọlọrun yóo sì gbá wọn lọ.
10. Olódodo yóo yọ̀ nígbà tí ẹ̀san bá ń ké,yóo fi ẹsẹ̀ wọ́ àgbàrá ẹ̀jẹ̀ àwọn eniyan burúkú.
11. Àwọn eniyan yóo wí nígbà náà pé,“Nítòótọ́, èrè ń bẹ fún olódodo;nítòótọ́, Ọlọrun ń bẹ tí ń ṣe ìdájọ́ ayé.”