20. wọ́n ń wí pé, ‘Dájúdájú, àwọn ọ̀tá wa ti parun,iná sì ti jó gbogbo ohun tí wọ́n fi sílẹ̀.’
21. “Nisinsinyii gba ti Ọlọrun,kí o sì wà ní alaafia;kí ó lè dára fún ọ.
22. Gba ìtọ́ni rẹ̀,kí o sì kó ọ̀rọ̀ rẹ̀ lékàn.
23. Bí o bá yipada sí Olodumare, tí o sì rẹ ara rẹ sílẹ̀,tí o bá mú ìwà aiṣododo kúrò ní ibùgbé rẹ,
24. bí o bá ri wúrà mọ́ inú erùpẹ̀,tí o fi wúrà Ofiri sí ààrin àwọn òkúta ìsàlẹ̀ odò,
25. bí Olodumare bá sì jẹ́ wúrà rẹ,ati fadaka olówó iyebíye rẹ,
26. nígbà náà ni o óo láyọ̀ ninu Olodumare,o óo sì lè dúró níwájú Ọlọrun.