61. Màríà Magidalénì àti Màríà kejì wà níbẹ̀, wọn jòkóò dojú kọ ibojì náà.
62. Lọjọ́ kejì tí ó tẹlé ọjọ́ ìpalẹ̀mọ́ àwọn olórí àlùfáà àti àwọn Farisí lọ sọ́dọ̀ Pílátù.
63. Wọ́n sọ fún un pé, “Alàgbà, ẹlẹ́tàn náà wí nígbà kan pé, ‘Lẹ́yìn ọjọ́ kẹta èmi yóò tún jí dìde.’
64. Nítorí náà, pàṣẹ kí a ti ibojì rẹ̀ gbọn-ingbọn-in títí ọjọ́ kẹta, kí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Rẹ̀ má ṣe wá jí i gbé lọ, wọn a sì bẹ̀rẹ̀ sí í sọ fún gbogbo ènìyàn pé, ‘Òun ti jíǹde,’ Bí èyí bá ní láti ṣẹlẹ̀, yóò burú fún wa púpọ̀ ju ti àkọ́kọ́ lọ.”