1. Nígbà náà ní àwọn Farisí àti àwọn olùkọ́ òfin tọ Jésù wá láti Jerúsálémù,
2. wọn béèrè pé, “Èé se tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ fi ń ṣe àìgbọ́ràn sí àwọn àṣà àtayébáyé Júù? Nítorí tí wọn kò wẹ ọwọ́ wọn kí wọ́n tó jẹun!”
3. Jésù sì dá wọn lóhùn pé, “È é ha ṣe tí ẹ̀yin fi rú òfin Ọlọ́run, nítorí àṣà yín?