48. Àwọn tó wà níbẹ̀ kígbe mọ́ ọn pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́.” Ṣùgbọ́n dípò kí ó pa ẹnu mọ́, ṣe ló ń kígbe lóhùn rara pé, “Jésù ọmọ Dáfídì ṣàánú fún mi.”
49. Nígbà tí Jésù gbọ́ igbe rẹ̀, ó dẹṣẹ̀ dúró lójú-ọ̀nà, ó sì wí pé, “Ẹ pè é kí ó wá sọ́dọ̀ mi.” Nítorí náà wọ́n pe ọkùnrin afọ́jú náà, wọ́n wí pé, “Tújúká!, dìde lórí ẹsẹ̀ rẹ! Ó ń pè ọ́.”
50. Lẹ́sẹ̀kan-náà, Bátíméù bọ́ aṣọ rẹ̀ sọnù, ó fò sókè, ó sì wá sọ́dọ̀ Jésù.
51. Jésù béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ìwọ fẹ́ kí èmi kí ó ṣe fún ọ?”Afọ́jú náà dáhùn pé, “Rábì, jẹ́ kí èmi ki o ríran.”