72. Láti ṣe àánú tí ó ti lérí fún àwọn baba wa,Àti láti rántí májẹ̀mu rẹ̀ mímọ́,
73. ìbúra tí ó ti bú fún Ábúráhámù baba wa,
74. láti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa,Kí àwa kí ó lè máa sìn ín láìfòyà,
75. Ní mímọ́ ìwà àti ní òdodo níwájú rẹ̀, ní ọjọ́ ayé wa gbogbo.
76. “Àti ìwọ, ọmọ mi, wòlíì Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó máa pè ọ́:Nítorí ìwọ ni yóò ṣáájú Olúwa láti tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe;