10. Nítorí tí èmí wà pẹ̀lú rẹ, kò sì sí ẹni tí yóò dìde sí ọ láti pa ọ lára: nítorí mo ní ènìyàn púpọ̀ ni ìlú yìí.”
11. Ó sì jókòó níbẹ̀ ní ọdun kan àti oṣù mẹ́fà, ó ń kọ́ni ní ọ̀rọ̀ Ọlọ́run láàrin wọn.
12. Nígbà tí Gálíónì sì jẹ báalẹ̀ Ákáyà, àwọn Júù fi ìfìmọ̀ṣọ̀kan dide sí Pọ́ọ̀lù wọn sì mú un wá síwájú ìtẹ́ ìdájọ́.