5. Baba àwọn aláìní baba àti Onídàájọ́ àwọn opó ni Ọlọ́run ni ibùgbéRẹ̀ mímọ́
6. Ọlọ́run gbé ẹni òfokálẹ̀ nínú ìdílé,ó darí àwọn ẹlẹ́wọ̀n pẹ̀lú orinṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ni ń gbé nínú ilẹ̀ gbígbẹ.
7. Nígbà tí ìwọ bá jáde lónìí níwájú àwọn ènìyàn Rẹ̀, Ọlọ́run,tí ń kọjá lọ láàrin ihà, Sela
8. Ilẹ̀ mi títí,àwọn ọ̀run ń rọ òjò jáde,níwájú Ọlọ́run,ẹni Sínáì,níwájú Ọlọ́run, Ọlọ́run Ísírẹ́lì.
9. Ìwọ fún wa ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò, Ọlọ́run;ìwọ tu ilé inú Rẹ̀ lára nígbà tí ó Rẹ̀ ẹ́ tan.
10. Àwọn ènìyàn Rẹ tẹ̀dó ṣíbẹ̀nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní Rẹ̀, Ọlọ́run, ìwọ pèsè fún àwọn aláìní.
11. Olúwa ti pàṣẹ ọ̀rọ̀,púpọ̀ ní ogun àwọn ẹni tí o ń ròyìn Rẹ.
12. “Àwọn ọba àti àwọn ológun yára sálọ;Obìnrín tí ó sì jókòó ni ilé ní ń pín ìkógun náà.
13. Nígbà tí ẹ̀yin sùn láàrin àwọn àgọ́ iná,nígbà náà ni ẹ̀yin ó dàbí apá àdàbà ti a bò ní sílífa.”
14. Nígbà ti Olódùmarè fọ́n àwọn ọba ká ní ilẹ̀ náà,ó dàbí òjò dídi ní Salímónì.
15. Òkè Básánì jẹ́ òkè Ọlọ́run;òkè tí ó ní orí púpọ̀ ní òkè Básánì.
16. Kí ló dé ti ẹ̀yin fi ń lára,ẹ̀yin òkè wúwo, òkè tí Ọlọ́run ti fẹ́ láti jọbaníbi tí Ọlọ́run fúnrarẹ̀ yóò máa gbé títí láé?
17. Ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní kẹ̀kẹ́ ogun Ọlọ́runẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; Olúwa ń bẹ láàrin wọn ní Sínáì ni ibi mímọ́ Rẹ̀.
18. Ìwọ ti gòkè sí ibi gígaìwọ ti di ìgbèkùn ní ìgbékùn lọ;ìwọ ti gbà ẹ̀bùn fún ènìyàn:nítòótọ́, fún àwọn ọlọ̀tẹ̀ pẹ̀lú,Kí Olúwa Ọlọ́run lè máa bá wọn gbé.
19. Olùbùkún ni Ọlọ́run,sí Ọlọ́run Olùgbàlà wa,ẹni tí ó ń fi ojojúmọ́ gba ẹrù wa rù. Sela
20. Ọlọ́run wa jẹ́ Ọlọ́run tó ń gbàlààti sí Olúwa Ọlọ́run ni ó ń gbà wá lọ́wọ́ ikú.
21. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò tẹ orí àwọn ọ̀tá Rẹ̀,àti agbárí onirun àwọn tó ń tẹ̀ṣíwájú nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn
22. Olúwa wí pé, “Èmi o mú wọn wá láti Báṣánì;èmi ó mú wọn wá láti ibú omi òkun,