14. Ó ta àwọn ọfà Rẹ̀, ó sì tú àwọn ọ̀ta náà ká,ọfà mọ̀nàmọ́ná ńlá sì dà wọ́n rú.
15. A sì fi ìṣàlẹ̀ àwọn òkun hàn,a sì rí àwọn ìpìlẹ̀ ayénípa ìbáwí Rẹ̀, Olúwa,nípa fífún èémí ihò imú Rẹ.
16. Ó sọ̀kalẹ̀ láti ibi gíga ó sì dì mí mú;Ó fà mí jáde láti inú omi jínjìn.
17. Ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ ọ̀ta mi alágbára,láti ọwọ́ àwọn ọ̀ta, ti ó lágbára jù fún mi.
18. Wọ́n dojúkọ mí ní ọjọ́ ìpọ́njú mi;ṣùgbọ́n Olúwa ni alàtìlẹ́yìn mi.
19. Ó mú mi jáde wá sínú ibi ńlá;Ó gbà mí nítorí tí ó ní inúdídùn sí mi.
20. Olúwa ti hùwà sí mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi;gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi, ó ti fi èrè fún mi
21. Nítorí mo ti pa ọ̀nà Olúwa mọ́;èmi kò ṣe búbúrú nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi
22. Gbogbo òfin Rẹ̀ ni ó wà níwájú mi;èmi kò sì yípadà kúrò nínú ìlànà Rẹ̀.
23. Mo ti jẹ́ aláìlẹ́bi níwájú Rẹ̀;mo sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.
24. Olúwa san ẹ̀ṣan fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi;gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi níwájú Rẹ̀.
25. Sí olóòótọ́ ìwọ ó fi ara Rẹ̀ hàn ní olóòtọ́,sí aláìlẹ́bi, ìwọ ó fi ara Rẹ̀ hàn ní aláìlẹ́bi,
26. Sí ọlọ́kan mímọ́, ìwọ ó fi ara Rẹ̀ hàn ní ọlọ́kàn mímọ́,ṣùgbọ́n sí ọlọ́kàn-wíwọ́, ìwọ ó fi ara Rẹ̀ hàn ní òǹrorò.
27. O pa onírẹ̀lẹ̀ mọ́,ṣùgbọ́n o Rẹ̀ àwọn ti ń gbéraga sílẹ̀.
28. Ìwọ, Olúwa, jẹ́ kí fìtílà mikí ó máa tàn; Ọlọ́run mi, yí òkùnkùn mi padà sí ìmọ́lẹ̀.
29. Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Rẹ̀, èmi ṣare la ogun lọ;pẹ̀lú Ọlọ́run mi mo lè fo odi kan
30. Bí ó ṣe ti Ọlọ́run mi, ọ̀nà Rẹ̀ pé,a ti rídìí ọ̀rọ̀ Olúwaòun ni àpáta ààbòfún gbogbo àwọn tí ó fi ṣe ààbò.
31. Nítorí ta ni ṣe Ọlọ́run bí kò ṣe Olúwa?Ta ní àpátà bí kò ṣe Olúwa wa?
32. Ọlọ́run ni ẹni tí ó fi agbára dì mí ní àmùrèó sì mú ọ̀nà mi pé.