26. Nítorí Olúwa yóò jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹkì yóò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ bọ́ sínú pàkúté.
27. Má ṣe fa ọwọ́ ire sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó tọ́ sí,nígbà tí ó bá wà ní ìkápá rẹ láti ṣe ohun kan.
28. Má ṣe wí fún aládùúgbò rẹ pé,“Padà wá nígbà tó ṣe díẹ̀; ó fún ọ lọ́lá”nígbà tí o ní i pẹ̀lú rẹ nísinsin yìí.
29. Má ṣe pète ohun búburú fún aládùúgbò rẹ,ti o gbé nítòsí rẹ, tí ó sì fọkàn tán ọ.
30. Má ṣe fẹ̀ṣùn kan ènìyàn láì-ní-ìdínígbà tí kò ṣe ọ́ ní ibi kankan rárá.
31. Má ṣe ṣe ìlara ènìyàn jàgídíjàgantàbí kí o yàn láti rìn ní ọ̀nà rẹ̀,
32. Nítorí Olúwa kórìíra ènìyàn aláyìídáyidàṣùgbọ́n a máa fọkàn tán ẹni dídúró ṣinṣin.
33. Ègún Olúwa ń bẹ lórí ilé ènìyàn búburú,ṣùgbọ́n ó bùkún fún ilé olódodo
34. Ó fi àwọn oníyẹ̀yẹ́ ṣe yẹ̀yẹ́Ṣùgbọ́n ó fi oore ọ̀fẹ́ fún onírẹ̀lẹ̀
35. ọlọ́gbọ́n jogún iyìṢùgbọ́n àwọn aláìgbọ́n ni ó dójú tì.