4. Ẹ̀mí Ọlọ́run Ní ó tí dá mi,Àti ìmísí Olódùmáre ni ó ti fún mi ní ìyè.
5. Bí ìwọ bá le dá mi lóhùn,tò ọ̀rọ̀ rẹ̀ lẹ́ṣẹẹsẹ níwájú mi; dìdé!
6. Kíyèsí i, bí ìwọ ṣe jẹ́ ti Ọlọ́run,bẹ́ẹ̀ ni èmí náà; láti amọ̀ wá ni a sì ti dá mi pẹ̀lú
7. Kíyèsí i, ẹrù ń lá mi kì yóò bà ọ;bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi kì yóò wúwo sí ọ lára.
8. “Nítòótọ́ ìwọ sọ ní etí mi, èmí sìgbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ wí pé,
9. ‘Èmí mọ́, laini ẹ̀ṣẹ̀ ìrékọjá;Àláìṣẹ̀ ní èmí; bẹ́ẹ̀ àìṣéédéé kò sí ní ọwọ́ mi.
10. Kíyèsí i, Ọlọ́run ti rí àìṣedéédéépẹ̀lú mi; ó kà mí sì ọ̀tá rẹ̀.
11. Ó kàn ẹ̀ṣẹ̀ mi sínú àbà; o kíyèsiipa ọ̀nà mi gbogbo.’
12. “Kíyèsí i, nínú èyí ìwọ sìnà! Èmí odá ọ lóhùn pé, Ọlọ́run tóbi jù ènìyàn lọ!
13. Nítorí kí ni ìwọ ṣe ń báa jà, wí pé,òun kò níi sọ ọ̀rọ̀ kan nítorí iṣẹ́ rẹ̀?
14. Nítorí pe Ọlọ́run sọ̀rọ̀ lẹ́ẹkan, ànílẹ́ẹkẹji, ṣùgbọn ènìyàn kò róye rẹ̀.