1. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremáyà wá nígbà tí Ọba Sedekáyà rán Páṣúrì ọmọ Málíkíjà àti àlùfáà Sedekáyà ọmọ Mánásè síi; wọ́n wí pé:
2. “Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadinésárì Ọba Bábílónì ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”