Àìsáyà 9:1 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)
Ṣíbẹ̀ṣíbẹ̀, kò ní sí ìpòrúurù kan kan mọ́ fún àwọn tí ó wà nínú ìbànújẹ́. Nígbà kan rí ó rẹ ilẹ̀ Sẹbúlúnì sílẹ̀ àti ilẹ̀ Nápítalì pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ iwájú, yóò bu ọ̀wọ̀ fún Gálílì ti àwọn aláìkọlà, ní ọ̀nà òkun, ní ẹ̀gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ Jọ́dánì.