2 Sámúẹ́lì 4:12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)
Dáfídì sì fi àṣẹ fún àwọn ọdọ́mọkùnrin rẹ̀, wọ́n sì pa wọ́n, wọ́n sì gé ọwọ́ àti ẹṣẹ̀ wọn, a sì fi wọ́n há lórí igi ní Hébírónì. Ṣùgbọ́n wọ́n mú orí Íṣíbóṣétì, wọ́n sì sin ín ní ibojì Ábínérì ní Hébírónì.