1. Nígbà tí Ṣọ́ọ̀lù padà kúrò lẹ́yìn àwọn Fílístínì a sì sọ fún un pé, “Wò ó, Dáfídì ń bẹ́ ni ihà Éńgédì.”
2. Ṣọ́ọ̀lù sì mú ẹgbẹ̀ẹ́dógún akọni ọkùnrin tí a yàn nínú gbogbo Ísírẹ́lì ó sì lọ láti wá Dáfídì àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ lorí òkúta àwọn ewúrẹ́ igbó.
3. Ó sì dé ibi àwọn agbo àgùntàn tí ó wà ní ọ̀nà, ihò kan sì wà níbẹ̀, Ṣọ́ọ̀lù sì wọ inú rẹ̀ lọ láti bo ẹṣẹ̀ rẹ̀, Dáfídì àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì ń bẹ lẹ́bàá ihò náà.