1. Dáfídì sì kúrò níbẹ̀, ó sì sá sí ihò Ádúlámù; nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ìdílé baba rẹ̀ sì gbọ́, wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá níbẹ̀.
2. Olúkúlùkù ẹni tí ó tí wà nínú ipọ́njú, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ti jẹ gbésè, àti olúkúlùkù ẹni tí ó wà nínú ìbànújẹ́, sì kó ara wọn jọ sọ́dọ̀ rẹ̀, òun sì jẹ́ olórí wọn; àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì tó iwọ̀n irinwó ọmọkùnrin.