1. Bẹni-Hádádì ọba Árámù sì gbá gbogbo ogun rẹ̀ jọ. Ọba méjìlélọ́gbọ̀n sì ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀ àti ẹsin àti kẹ̀kẹ́, ó sì gòkè lọ, ó sì dóti Samáríà, ó sì kọlù ú.
2. Ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Áhábù ọba Ísírẹ́lì wí pé, “Báyìí ni Bẹni-Hádádì wí:
3. Sílífà àti wúrà rẹ tèmi ni, àti àwọn tí ó dára jùlọ nínú àwọn aya re àti àwọn ọmọ rẹ tèmi ni wọ́n.”