8. Ábíjà sì sùn pẹ̀lú àwọn bàbá rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dáfídì. Áṣà ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.
9. Ní ogún ọdún Jéróbóámù ọba Ísírẹ́lì, Áṣà jọba lórí Júdà,
10. Ó sì jọba ní Jérúsálẹ́mù ní ọdún mọ́kànlélógójì. Orúkọ ìyá ìyá rẹ̀ sì ni Máákà, ọmọbìnrin Ábúsálómù.