5. Nítorí tí Dáfídì ṣe èyí tí ó dára ní ojú Olúwa, tí kò sì kùnà láti pa gbogbo èyí tí Olúwa pa láṣẹ fún un mọ́ ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo; bí kò ṣe ní kìkì ọ̀ràn Ùráyà ará Hítì.
6. Ogun sì wà láàrin Réhóbóámù àti Jéróbóámù ní gbogbo ọjọ́ ayé Ábíjà.
7. Níti ìyókù ìṣe Ábíjà, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, a kò há kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Júdà? Ogun sì wà láàrin Ábíjà àti Jéróbóámù.
8. Ábíjà sì sùn pẹ̀lú àwọn bàbá rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dáfídì. Áṣà ọmọ rẹ̀ sì jọba ní ipò rẹ̀.
9. Ní ogún ọdún Jéróbóámù ọba Ísírẹ́lì, Áṣà jọba lórí Júdà,
10. Ó sì jọba ní Jérúsálẹ́mù ní ọdún mọ́kànlélógójì. Orúkọ ìyá ìyá rẹ̀ sì ni Máákà, ọmọbìnrin Ábúsálómù.
11. Áṣà sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, bí Dáfídì baba rẹ̀ ti ṣe.